Léfítíkù 26:4-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Èmi yóò rọ̀jò fún yín ní àkókò rẹ̀, kí ilẹ̀ yín le mú èso rẹ̀ jáde bí ó tí yẹ kí àwọn igi eléso yín so èso.

5. Èrè oko yín yóò pọ̀ débí pé ẹ ó máa pa ọkà títí di àsìkò ìkórè igi eléso, ẹ̀yin yóò sì máa gbé ní ilé yín láì léwu.

6. “ ‘Èmi yóò fún yín ní àlàáfíà ní ilẹ̀ yín, ẹ̀yin yóò sì sùn láìsí ìbẹ̀rù ẹnikẹ́ni. Èmi yóò mú kí gbogbo ẹranko búburú kúrò ní ilẹ̀ náà: bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sì sí ogun mọ́.

7. Ẹ̀yin yóò lé àwọn ọ̀ta yín: wọn yóò sì tipa idà kú.

8. Àwọn márùn-ún péré nínú yín yóò máa sẹ́gun ọgọ́rùn-ún ènìyàn: Àwọn ọgọ́rùn-ún yóò sì máa sẹ́gun ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá: Àwọn ọ̀ta yín yóò tipa idà kú níwájú yín.

Léfítíkù 26