Léfítíkù 14:25-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Kí ó pa ọ̀dọ́ àgùntàn ẹbọ ẹ̀bi kí ó sì mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Kí ó fi sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí a ó ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún.

26. Àlùfáà yóò sì da díẹ̀ lára òróró náà sí àtẹ́lẹwọ́ osì ara rẹ̀.

27. Yóò sì fi ìka ìfábẹ̀lá ọ̀tún rẹ̀ wọ́n òróró tí ó wà ní àtẹ́lẹwọ́ òsì rẹ̀ nígbà méje níwájú Olúwa.

28. Àlùfáà yóò sì mú lára òróró ọwọ́ rẹ̀ sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹṣẹ̀ ọ̀tún ẹni tí a ń ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún ní ibi kan náà tí wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi sí.

29. Kí àlùfáà fi ìyókù nínú òróró ọwọ́ rẹ̀ sí orí ẹni náà tí a ń ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún: láti ṣe ètùtù fún un ní ìwájú Olúwa.

30. Lẹ́yìn náà kí ó fí àdàbà tàbí ọmọ ẹyẹlé rúbọ níwọn ti agbára rẹ̀ mọ.

31. Ọ̀kan fún ẹbọ ẹṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ ẹ̀bi pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ: Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù níwájú Olúwa ní ìpò ẹni tí a fẹ́ wẹ̀ mọ́.”

Léfítíkù 14