Jóòbù 32:15-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. “Ẹnu sì yà wọ́n, wọn kò sì dáhùnmọ́, wọ́n síwọ́ ọ̀rọ̀ ísọ́.

16. Mo si reti, nítorí wọn kò sìfọhún, wọ́n dákẹ́ jẹ́ẹ́; wọn kò sì dáhùn mọ́.

17. Bẹ́ẹ̀ ni èmí ò sì dáhùn nípa tièmí, èmí pẹ̀lú yóò sì fi ìmọ̀ mi hàn.

18. Nítorí pé èmí kún fún ọ̀rọ̀ sísọ,èmí ń rọ̀ mi ni inú mi.

19. Kíyèsí i, ìkùn mi dàbí ọtí wáìnì,tí kò ní ojú-ìhò; ó múra tán láti bẹ́ bí ìgò-àwọ̀ tuntun.

20. Èmí ó sọ, kí ara kí ó le rọ̀ mí,èmí ó sí ètè mi, èmí ó sì dáhùn.

21. Lótítọ́ èmí kì yóò ṣe ojúṣàájú síẹnìkankan, bẹ́ẹ̀ ni èmí kì yóò sì ṣe ìpọ́nni fún ẹnìkan.

Jóòbù 32