5. Wọ́n sì dá a lóhùn wí pé, “Jésù ti Násárétì.”Jésù sì wí fún wọn pé, “Èmi nìyí.” (Àti Júdásì ọ̀dàlẹ̀, dúró pẹ̀lú wọn.)
6. Nítorí náà bí ó ti wí fún wọn pé, “Èmi nìyí, wọ́n bì sẹ́yìn, wọ́n sì ṣubú lulẹ̀.”
7. Nítorí náà ó tún bi wọ́n léèrè, wí pé, “Ta ni ẹ ń wá?”Wọ́n sì wí pé, “Jésù ti Násárétì.”
8. Jésù dáhùn pé, “Mo ti wí fún yín pé, èmi nìyí: ǹjẹ́ bí èmi ni ẹ bá ń wá, ẹ jẹ́ kí àwọn wọ̀nyí máa lọ: