20. Àwọn Gíríkì kan sì wà nínú àwọn tí ó gòkè wá láti sìn nígbà àjọ:
21. Àwọn wọ̀nyí ni ó tọ Fílípì wá, ẹni tí í ṣe ará Bẹtisáídà tí Gálílì, wọ́n sì ń bèèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Alàgbà, àwa ń fẹ́ rí Jésù!”
22. Fílípì wá, ó sì sọ fún Ańdérù; Ańdérù àti Fílípì wá, wọ́n sì sọ fún Jésù.
23. Jésù sì dá wọn lóhùn pé, “Wákàtí náà dé, tí a ó ṣe Ọmọ ènìyàn lógo.
24. Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí kò ṣe pé àlìkámà bá bọ́ sí ilẹ̀, tí ó bá sì kú, ó wà ní òun nìkan; ṣùgbọ́n bí ó bá kú, a sì so ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso.