7. Gẹ́gẹ́ bí kàǹga ṣe ń da omi inú rẹ̀ sílẹ̀,náà ni ó ń tú ìwà búburú rẹ̀ jáde.Ìwà ipá àti ìparun ń tún dún padà nínú rẹ̀;nígbà gbogbo ni àìsàn àti ọgbẹ́ rẹ̀ ń wà níwájú mi.
8. Ìwọ Jérúsálẹ́mù, gba ìkìlọ̀kí Èmi kí ó má ba à lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ,kí n sì sọ ilẹ̀ rẹ di ahoro,tí kò ní ní olùgbé.”
9. Èyí ni ohun tí Olúwa Àwọn ọmọ ogun wí:“Jẹ́ kí wọn pesẹ́ ìyókù Ísírẹ́lìní tónítóní bí àjàrà;na ọwọ́ rẹ sí àwọn ẹ̀ka nì lẹ́ẹ̀kan sí igẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti í kó èṣo àjàrà jọ.”
10. Ta ni ẹni tí mo lè bá sọ̀rọ̀ àtití mo lè fún ní ìmọ̀ràn? Ta niyóò tẹ́tí sílẹ̀ sí mi? Etí wọnti di, nítorí náà wọn kò lè gbọ́.Ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ ohun búburú sí wọn,wọn kò sì ní inú dídùn nínú rẹ̀.
11. Èmi kún fún ìbínú Olúwa, èmi kò sì le è pa á mọ́ra.“Tú u sí orí àwọn ọmọ ńigboro, àtisórí àwọn ọmọkùnrin tí wọn kórawọn jọ pọ̀, àti ọkọ àti aya ni a òmú sínú rẹ̀, àti àwọn arúgbótí ó ní ọjọ́ kíkún lórí.