21. Nítorí náà, èyi ni ohun tí Olúwa wí:“Èmi yóò gbé ohun ìdènà ṣíwájúàwọn ènìyàn wọ̀nyí, àwọn bàbáàti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n,àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”
22. Èyí ni Olúwa wí:“Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá,a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìdeláti òpin ayé wá.
23. Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀,Wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánúwọ́n ń hó bí omi òkun, bí wọ́nti ṣe ń gun àwọn ẹsin wọn lọ;wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóòjà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Síónì.”
24. Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn,ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wabí ìrora bí obìnrin tí í rọbí.