Jeremáyà 38:14-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Nígbà náà ni Ọba Sedekáyà ránṣẹ́ pe, Jeremáyà òjíṣẹ́ Ọlọ́run àti láti mú un wá sí ẹnubodè kẹta nílé Ọlọ́run. Ọba sì sọ fún Jeremáyà pé, “Èmi yóò bi ọ́ ní ohun kan; má sì ṣe fi ohun kan pamọ́ fún mi.”

15. Jeremáyà sì sọ fún Sedekáyà pé, “Tí mo bá fún ọ ní èsì, ṣé o kò ní pa mí? Tí mo bá gbà ọ́ nímọ̀ràn, o kò ní gbọ́ tèmi.”

16. Ṣùgbọ́n Ọba Sedekáyà búra ní ìkọ̀kọ̀ fún Jeremáyà wí pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti ń bẹ, ẹni tí ó fún wa ní ẹ̀mí, èmi kò ní pa ọ́ tàbí fà ọ́ fún àwọn tó ń lépa ẹ̀mí rẹ.”

17. Nígbà náà ni Jeremáyà sọ fún Sedekáyà pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run alágbára, Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí: ‘Àyàfi bí o bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn olóyè Ọba Bábílónì, a ó dá ẹ̀mí rẹ sí àti pé ìlú yìí kò ní di jíjó níná; ìwọ àti ilé rẹ yóò sì wà láàyè.

18. Ṣùgbọ́n tí o kò bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn ìjòyè Ọba Bábílónì, a ó fa ìlú yìí lé ọwọ́ àwọn Bábílónì. Wọn yóò sì fi ina sun-un, ìwọ gan-an kò ní le sá mọ́ wọn lọ́wọ́.’ ”

Jeremáyà 38