1. Nígbà tí Nebukadinésárì Ọba Bábílónì àti àwọn ọmọ ogun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ Ọba tí ó jọba lé lórí ń bá Jérúsálẹ́mù jà, àti gbogbo àwọn ìlú tí ó yí ká, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremáyà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa pé:
2. “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì ọmọ ogun wí: Lọ sí ọ̀dọ̀ Sedekáyà Ọba Júdà kí o sì sọ fún-un pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Èmi fẹ́ fa orílẹ̀ èdè yìí lé Ọba Bábílónì lọ́wọ́, yóò sì jó palẹ̀.
3. Ìwọ kò ní sá àsálà, ṣùgbọ́n à ó mú ọ, bẹ́ẹ̀ ni a ó sì fà ọ́ lé e lọ́wọ́. Ìwọ yóò rí Ọba Bábílónì pẹ̀lú ojú ara rẹ; yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ lójúkojú; ìwọ yóò sì lọ sí Bábílónì.