Jeremáyà 25:22-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Gbogbo àwọn Ọba Tirè àti Sídónì; gbogbo àwọn Ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá òkun.

23. Dédánì, Témà, Búsì àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jínjìn réré.

24. Gbogbo àwọn Ọba Árábíà àti àwọn Ọba àwọn àjòjì ènìyàn tí ń gbé inú ihà.

25. Gbogbo àwọn Ọba Símírì, Élámù àti Mídíà.

26. Àti gbogbo àwọn Ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jínjìn, ẹnìkìn-ín-ní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, Ọba Ṣéṣákì náà yóò sì mu.

Jeremáyà 25