Jeremáyà 23:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé,‘Olúwa ti wí pé: Ẹ ó ní àlàáfíà,’Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé,‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’

18. Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúrónínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí itàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀?Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?

19. Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jádepẹ̀lú ìbínú àfẹ́yíká ìjì yóò fẹ́ síorí àwọn olùṣe búburú.

20. Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ,ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.

21. Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyísíbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn.Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀,síbẹ̀ wọ́n sọ àṣọtẹ́lẹ̀,

22. Ṣùgbọ́n ìbáṣepọ̀ wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi,wọn ì bá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi.Wọn ì bá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi sí àwọn ènìyànwọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nààti ìṣe búburú wọn.

Jeremáyà 23