Jeremáyà 17:6-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá,kò ní rí ire, nígbà tí ó bá dé yóòmáa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ ihà,ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.

7. “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrinnáà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.

8. Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadòtí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odòkò sí ìbẹ̀rù fún-un nígbà ooru,gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutùkò sí ìjáyà fún-un ní ọdún ọ̀dábẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”

9. Ọkàn kún fún ẹ̀tàn ju ohungbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lèwòsàn, tani èyí lè yé?

10. “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èròinú ọmọ ènìyàn láti ṣan èrèiṣẹ́ rẹ̀ fún-un, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”

11. Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé niọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ niọ̀nà àìsòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti níòpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.

12. Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ní ibi ilé mímọ́ wa.

13. Olúwa olùgbẹ́kẹ̀lé Ísírẹ́lìgbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ niojú ó tì: gbogbo àwọn tí ó padàṣẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ọ́ kọorúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́nti kọ Olúwa orísun omi ìyè wọn sílẹ̀.

Jeremáyà 17