Jeremáyà 17:17-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ niààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú

18. Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi,ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínúìtìjú, jẹ́ kí wọn ó bẹ̀rù. Múọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparunìlọ́po méjì pa wọ́n run.

19. Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn Ọba Júdà ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu bodè Jérúsálẹ́mù.

20. Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin Ọba Júdà àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Júdà àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jérúsálẹ́mù tí ń wọlé láti ẹnu-bodè yìí.

Jeremáyà 17