Jẹ́nẹ́sísì 33:1-2 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jákọ́bù sì gbójú sókè, ó sì rí Ísọ̀ àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Líà, Rákélì àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.

2. Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn ṣíwájú, Líà àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rákélì àti Jóṣẹ́fù sì wà lẹ́yìn pátapáta.

Jẹ́nẹ́sísì 33