Jẹ́nẹ́sísì 23:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Éfúrónì ará Hítì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú, ó sì dá Ábúráhámù lóhùn lójú gbogbo àwọn ará ìlú tí ó wà níbẹ̀, lẹ́nu ibodè ìlú,

11. pé, “Rárá, Olúwa mi, Gbọ́ tèmi; mo fún ọ ní ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà níbẹ̀. Mo fún ọ níwájú gbogbo àwọn ènìyàn mi. Sin òkú rẹ ṣíbẹ̀.”

12. Ábúráhámù sì tún tẹríba níwájú àwọn ènìyàn ìlú náà,

13. Ó sì wí fún Éfúrónì lójú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, gbọ́ tèmi, èmi yóò san owó ilẹ̀ náà, gbà á lọ́wọ́ mi kí n lè sin òkú mi ṣíbẹ̀.”

14. Éfúrónì sì dá Ábúráhámù lóhùn pé,

Jẹ́nẹ́sísì 23