Ísíkẹ́lì 40:41-46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

41. Nítorí náà, tẹ́ḿpìlì mẹ́rin ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ kan ẹnu ọ̀nà, mẹ́rin sì wà ní ẹ̀gbẹ́ kejì tẹ́ḿpìlì, mẹ́jọ ni gbogbo rẹ̀ lórí èyí ni a ti ń pa ohun ìrúbọ.

42. Tẹ́ḿpìlì mẹ́rin tí à fi òkúta ṣe lọ́sọ̀ọ́ sì tún wà fún ẹbọ sísun, ọ̀kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀ ni gígùn, ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀ ní fífẹ̀ àti ìgbọ̀nwọ́ kan ni gíga. Ní orí rẹ̀ ni a kó àwọn ohun èlò fún pípa, ọrẹ ẹbọ sísun àti àwọn ìrubọ tí ó kù sí.

43. Ìlọ́po méjì ohun èlò bí àmúga tí o ní ìwọ̀ tí ọ̀kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìbú ọwọ́ ní gígùn, ni a so mọ́ ara ògiri yíká. Àwọn tẹ́ḿpìlì náà wa fún ẹran ohun ìrúbọ.

44. Lẹ́yìn náà ó wọn àgbàlá: Ó jẹ́ ọgọ́rùn-ún ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn, ó sì jẹ́ ọgọ́rùn-ún ìgbọ̀nwọ́ ní fífẹ. Pẹpẹ sì wà ní iwájú tẹ́ḿpìlì.

45. Ó sì wí fún mi pé, “yàrá yìí, tí iwájú rẹ̀ wà níhà gúsù, wà fún àwọn àlùfáà, àwọn ti n bojútó ilé náà.

46. Iyàrá ti iwájú rẹ̀ ti o wà níhà àríwá, wà fún àwọn àlúfáà, àwọn ti ń bojútó pẹpẹ náà, àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Sádókù nínú àwọn ọmọ Léfì, tí wọ́n ń súnmọ́ Olúwa láti ṣe ìránṣẹ́ fún un.”

Ísíkẹ́lì 40