Ísíkẹ́lì 16:26-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. O ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Éjíbítì tí í ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ aládúgbò rẹ láti mú mi bínú pẹ̀lú ìwà àgbèrè rẹ tó ń pọ̀ sí i.

27. Nítorí náà ni mo fi na ọwọ mi lòdì sí ọ, mo ge ilé rẹ kúrú; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to korìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Fílístínì ti ìwàkiwà rẹ̀ jẹ ìyàlẹ́nu fún,

28. Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ o ṣàgbérè pẹ̀lú ara Ásíríà; síbẹ̀ náà, o kò tún ní ìtẹ́lọ́rùn.

29. Ìwà àgbèrè rẹ tún tẹ̀ṣíwájú dé ilẹ̀ oniṣòwò ni Bábílónì síbẹ̀ náà, o kò tún ni ìtẹ́lọ́rùn.

30. “Olúwa Ọlọ́run wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o n ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbérè!

31. Nígbà tí o kọ́lé funra rẹ, tóo sì tún kọ ojúbọ gíga si gbogbo òpin ojú pópó síbẹ̀, o ko tún ṣe bi àwọn alágbèrè gidi nítorí pé o kọ̀ láti gbowó

32. “ ‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!

Ísíkẹ́lì 16