3. Nítorí nípa ọtí wáìnì ìrunú àgbèrè rẹ̀ nigbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ṣubú.Àwọn ọba ayé sì ti bá a ṣe àgbèrè,àti àwọn oníṣòwò ayé sì di ọlọ́rọ̀ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọ̀bìà rẹ̀.”
4. Mo sì gbọ́ ohùn mìíràn láti ọ̀run wá, wí pé:“Ẹ ti inú rẹ̀ jáde, ẹ̀yin ènìyàn mi,kí ẹ ma bàá ṣe alábàápín nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,kí ẹ ma bàá si ṣe gbà nínú ìyọnu rẹ̀.
5. Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ ga títí dé ọ̀run,Ọlọ́run sì ti rántí àìsedédé rẹ̀.
6. San an fún un, àní bí òun tí san án fún ní,kí ó sì ṣe e ni ìlọ́po méjì fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀Nínú ago náà tí o ti kún, òun ni kí ẹ sì kún fún un ni méjì.