Ìfihàn 12:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. A sì lé dírágónì ńlá náà jáde, ejò láéláé ni, tí a ń pè ni Èṣù, àti Sàtanì, tí ń tan gbogbo ayé jẹ: a sì lé e jù sí ilẹ̀ ayé, a sì lé àwọn ańgẹ́lì rẹ̀ jáde pẹ̀lú rẹ̀.

10. Mo sì gbọ́ ohùn rara ní ọ̀run, wí pè:“Nígbà yìí ni ìgbàlà dé, àti agbára, àti ìjọba Ọlọ́run wá,àti ọlá àti Kírísítì rẹ̀.Nítorí a tí le olùfisùn àwọn arakùnrin wa jáde,tí o ń fí wọ́n sùn níwájú Ọlọ́run wa lọ́sàn-án àti lóru.

11. Wọ́n sì ti ṣẹ́gun rẹ̀nítorí ẹ̀jẹ̀ ọ̀dọ́-Àgùntàn náà,àti nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀rí wọn,wọn kò sì fẹ́ràn ẹ̀míwọn àní títí dé ikú.

12. Nítorí náà ẹ máa yọ̀, ẹ̀yin ọ̀run,àti ẹ̀yin tí ń gbé inú wọn.Ègbé ni fún ayé àti òkun;nítorí Èṣù sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá ní ìbínú ńlá,nítorí ó mọ̀ pé ìgbà kúkúrú ṣá ni òun ní.”

13. Nígbà tí dírágónì náà rí pé a lé òun lọ sí ilẹ ayé, ó sè inúnibíni sì obìnrin tí ó bí ọmọkùnrin náà.

Ìfihàn 12