Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7:11-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. “Ìyàn kan sì mú ni gbogbo ilẹ̀ Íjíbítì àti ni Kénánì, àti ìpọ́njú ńlá, àwọn baba wa kò sì rí oúnjẹ.

12. Ṣùgbọ́n nígbà tí Jákọ́bù gbọ́ pé Àlìkámà ń bẹ ni Íjíbítì, ó rán àwọn baba wa lọ lẹ́ẹ̀kínní.

13. Nígbà kejì Jósẹ́fù fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀, a sì tún fi wọ́n hàn fún Fáráò.

14. Lẹ́yìn èyí, Jósẹ́fù ránsẹ́ pe Jákọ́bù baba rẹ̀, àti àwọn ìbátan rẹ̀ wá sọ̀dọ̀ rẹ, gbogbo wọ́n sì tó àrúndínlọ́gọ́rin ènìyàn.

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7