25. Bí Pọ́ọ̀lù sì tí ń sọ àsọyé nípa tí òdodo àti àìrékọjá àti ìdájọ́ tí ń bọ̀, ẹ̀rù ba Fẹ́líkísì, ó dáhùn wí pé, “Èyí tí o sọ nì tó ná! Máa lọ nísinsìn yìí ná. Nígbà tí mo bá sì ní àkókò tí ó wọ̀, èmi ó ránṣẹ́ pè ọ́.”
26. Ní àkókó yìí kan náà, ó ń retí pẹ̀lú pé Pọ́ọ̀lù yóò mú owó-ẹ̀yìn wá fún òun, kí òun baà lè dá a sílẹ̀: nítorí náà, a sì máa ránṣẹ́ sì í nígbàkúgbà, a máa bá a sọ̀rọ̀.
27. Lẹ́yìn ọdun méjì, Póríkíúsì Fẹ́sítúsì rọ́pò Fẹ́líkísì: Fẹ́líkísì ṣí ń fẹ́ se ojú rere fún àwọn Júù, ó fí Pọ́ọ̀lù sìlẹ́ nínú túbú.