Ìṣe Àwọn Àpósítélì 22:6-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. “Bí èmi tí súnmọ́ etí Dámásíkù níwọ̀n ọjọ́kanrí, lójijì ìmọ́lẹ̀ ńlá láti ọ̀run wá mọ́lẹ̀ yí mi ká.

7. Mo sì subú lulẹ̀, mo sì gbọ́ ohùn kan tí ó wí fún mi pé, ‘Ṣọ́ọ̀lù, Ṣọ́ọ̀lù èé ṣe tí ìwọ fi ń ṣe inúnibíni sí mi?’

8. “Mo sì béèrè pé, ‘Ta ni ìwọ́, Olúwa?’“Ó sì dá mi lóhùn pé, ‘Èmi ni Jésù tí Násárétì, ẹni tí ìwọ́ ń ṣe inúnibíni sí.’

9. Àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú mi rí ìmọ́lẹ̀ náà nítòótọ́, ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ohùn ẹni tí ń bá mi sọ̀rọ̀.

10. “Mo sí béèrè pé, ‘Kín ni kí èmí kí ó ṣe, Olúwa?’“Olúwa sì wí fún mi pé, ‘Dìde, kí o sì lọ sí Dámásíkù; níbẹ̀ ni a ó sì ti sọ ohun gbogbo fún ọ tí a yàn fún ọ láti ṣe.’

11. Àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú mi fà mí lọ́wọ́ wọ Dámásíkù lọ nítorí tí èmi kò lè ríran nítorí ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ náà ti fọ́ mi ní ojú.

12. “Ọkùnrin kan tí a ń pè ní Ananáyà tọ̀ mí wá, ẹni tó jẹ́ olùfọkànṣìn ti òfin, tí ó sì lórúkọ rere lọ́dọ̀ gbogbo àwọn Júù tí ó ń gbé ibẹ̀.

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 22