1. ÀWỌN ọkùnrin kan tí Jùdíà sọ̀kalẹ̀ wá, wọ́n sì kọ́ àwọn arakùnrin pé, “Bí kò ṣe pé a bá kọ yín ni ilà bí ìṣe Mósè, ẹ̀yin kí yóò lè là.”
2. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù àti Bánabà ni ìyapa àti ìyàn jíjà tí kò mọ níwọ̀n pẹ̀lú wọn, wọ́n yan Pọ́ọ̀lù àti Bánábà àti àwọn mìíràn nínú àpósítélì kí wọn gòkè lọ sí Jerúsálémù, sọ́dọ̀ àwọn alàgbà nítorí ọ̀ràn yìí.