Hósíà 14:6-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Àsẹ̀sẹ̀yọ ẹ̀ka rẹ̀ yóò dàgbà,Didan ẹwà yóò rẹ̀ dànù bí igi ólífìÒórùn rẹ yóò sì dàbí igi sídà ti Lébánónì.

7. Àwọn ènìyàn yóò tún padà gbé lábẹ́ òjijì rẹ̀.Yóò rúwé bi ọkà.Yóò sì yọ ìtànná bi àjàrà,òórùn rẹ yóò dàbí ti wáìnì Lébánónì.

8. Ìwọ Éfúráímù; Kín ló tún kù tí mo ní ṣe pẹ̀lú ère òrìṣà?Èmi ó daba! lóhùn, èmi o sì ṣe ìtọ́jú rẹ.Mo dàbí igi tó ń fi gbogbo ìgbà tutù,èso tí ìwọ ń so si ń wá láti ọ̀dọ̀ mi.”

9. Ta ni ọlọgbọ́n? Òun yóò mòye àwọn nǹkan wọ̀nyíTa a ní ó mọ̀? Òun yóò ní ìmọ̀ wọn.Tí tọ́ ni ọ̀nà Olúwaàwọn olódodo si ń rìn nínú wọnṢùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ nìyóò kọsẹ̀ nínú wọn.

Hósíà 14