Fílípì 1:26-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. kí ìbádàpọ̀ mi pẹ̀lú yín lẹ́ẹ̀kan si le ru ayọ̀ yín sókè nínú Kírísítì nítorí mi.

27. Ohun tó wù kí ó ṣẹlẹ̀, ẹ jẹ́ kí iṣẹ́ yín wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyìnrere Kírísítì. pé yálà bí mo tilẹ̀ wá wò yín, tàbí bí èmi kò wá, kí èmi lè máa gbúròó bí ẹ ti ń ṣe, pé ẹ̀yin dúró ṣinṣin nínú Ẹ̀mí kan, ẹ̀yin sì jùmọ̀ n jìjàkadì nítorí ìgbàgbọ́ ìyìn rere, pẹ̀lú ọkàn kan;

28. láìsí ìbẹ̀rẹ̀ àwọn tí ó dojúkọ yin lọ́nà kanna. Èyí sì jẹ́ àmì fún wọn pé a ó pa wọ́n run, a ó sì gbà yín là —èyí tí Ọlọ́run yí ó ṣe.

29. Nítorí a ti fi fún yín nítorí Kírísítì, kì í ṣe láti gbàgbọ́ nínú rẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n láti jìyà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú.

30. Nípa níní ìjàkadì kan náà tí ẹ̀yin ti rí tí èmi là kọjá, ti ẹ sì gbọ́ nísinsinyìí pé mo sì wà nínú rẹ̀.

Fílípì 1