1. Èmi Pọ́ọ̀lù, ẹni tí a fi sẹ́wọ̀n nítorí pé ó ń wàásù ìyìn rere Jésù Kírísítì àti Tímótíù arákùnrin wa.Sí Fílímónì ọ̀rẹ́ wa ọ̀wọ́n àti alábàáṣiṣẹ́ wa,
2. sí Áfíà arábìnrin wa, sí Ákípọ́sì ẹni tó jẹ́ jagunjagun fún àgbélébùú náà àti sí ìjọ àwọn Kírísítẹ́nì tí ó ń pàdé nínú ilé rẹ:
3. Oore-Ọ̀fẹ́ fún un yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti Jésù Kírísítì.
4. Èmi máa ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nígbà tí mo bá rántí rẹ nínú àdúrà mi,
5. nítorí mo ń gbọ́ nípa ìgbàgbọ́ rẹ nínú Jésù Olúwa àti nípa ìfẹ́ rẹ sí àwọn ènìyàn mímọ́.