Ẹ́sítà 5:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Hámánì jáde lọ ní ọjọ́ náà pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó rí Módékáì ní ẹnu ọ̀nà ọba, ó wòye pé kò dìde tàbí kí ó bẹ̀rù ní iwájú oun, inú bí i gidigidi sí Módékáì.

10. Ṣùgbọ́n, Hámánì kó ara rẹ̀ ní ìjánu, ó lọ sí ilé.Ó pe àwọn ọ̀rẹ́ẹ rẹ̀ jọ àti Sérésì ìyàwóo rẹ̀,

11. Hámánì gbéraga sí wọn nípa títóbi ọ̀rọ̀ rẹ̀, púpọ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ọ̀nà tí ọba ti bu ọla fún-un àti bí ó ṣe gbé e ga ju àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè tó kù lọ.

12. Hámánì tún fi kún-un pé, “Kìí ṣe èyí nìkan. Èmi nìkan ni ayaba Ẹ́sítà pè láti sin ọba wá sí ibi àsè tí ó sè. Bákan náà, ó sì tún ti pè mí pẹ̀lú ọba ní ọ̀la.

13. Ṣùgbọ́n gbogbo èyí kò ì tíì tẹ́ mi lọ́rùn níwọ̀n ìgbà tí mo bá sì ń rí Módékáì aráa Júù yẹn tí ó ń jòkòó lẹ́nu ọ̀nà ọba.”

Ẹ́sítà 5