Ẹ́sírà 8:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Nígbà náà ni mo yà àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣérébáyà, Hásábáyà àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,

25. Mo sì fi òṣùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀, awọn ìjòyè àti gbogbo ọmọ Ísírẹ́lì tí ó wà níbẹ̀ gbe fi sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.

26. Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀talẹ̀láàdọ́ta (650) talẹ́ńtì sílifà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn ún talẹ́ńtì, talẹ́ńtì wúrà

27. ogún (20) bóòlù wúrà (kílòmítà mẹ́jọ ààbọ̀) tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún (1,000) dárìkì, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí, bí i wúrà.

28. Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohum èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Sílífà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.

Ẹ́sírà 8