Ékísódù 3:4-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Nígbà tí Olúwa rí i pe Mósè ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárin igbó náà, “Mósè! Mósè!!”Mósè sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nì yìí.”

5. Ọlọ́run sì wí fún Mósè pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”

6. Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba yín, Ọlọ́run Ábúráhámù, Ọlọ́run Ísáákì àti Ọlọ́run Jákọ́bù.” Nítorí ìdí èyí, Mósè fi ojú rẹ̀ pamọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti wo ojú Ọlọ́run.

Ékísódù 3