1. Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mósè pé, “Gòkè tọ Olúwa wá, ìwọ àti Árónì, Nádábú àti Ábíhù àti àádọ́rin (70) àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì. Ẹ̀yin kì ó sìn ni òkèèrè réré.
2. Ṣùgbọ́n Mósè nìkan ṣoṣo ni yóò súnmọ́ Olúwa; àwọn tókù kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí ibẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò gbọdọ̀ gòkè wá pẹ̀lú rẹ̀.”
3. Nígbà ti Mósè lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn, gbogbo ọ̀rọ̀ àti òfin Olúwa, wọ́n wí ní ohùn kan pé, “Gbogbo ohun ti Olúwa wí ni àwa yóò ṣe.”