Ékísódù 21:28-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. “Bí akọ màlúù bá kan ọkùnrin tàbí obìnrin kan pa, a ó sọ akọ màlúù náà ní òkúta pa, a kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀. Ṣùgbọ́n a kò ní dá ẹni tí ó ni akọ màlúù náà lẹ́bi, ọrùn rẹ̀ yóò sì mọ́.

29. Ṣùgbọ́n tí ó bá ti di ìgbà gbogbo ti akọ màlúù náà ti máa ń kan ènìyàn, tí a sì ti ń kìlọ̀ fún olówó rẹ̀, ti olówó rẹ̀ kò sì mú un so, tí ó bá kan ọkùnrin tàbí obìnrin pa, a ó sọ akọ màlúù náà ní òkúta pa, a ó sì pa olówó rẹ̀ pẹ̀lú.

30. Bí àwọn ará ilé ẹni tí ó kú bá béèrè fún owó ìtanràn, yóò san iye owó tí wọ́n bá ní kí ó san fún owó ìtanràn láti fi ra ẹ̀mí araarẹ̀ padà.

31. Bí akọ màlúù bá kan ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin pa, a ó se gẹ́gẹ́ bí ofin yìí ti là á kalẹ̀.

32. Bí akọ màlúù bá kan ẹrúkùnrin tàbí ẹrúbìnrin pa, olówó rẹ̀ yóò san ọgbọ̀n sékélì fàdákà fún ẹni tó ni ẹrú, a ó sì sọ akọ màlúù náà ni okúta pa.

Ékísódù 21