Deutarónómì 28:52-55 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

52. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú ù rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú ù rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.

53. Nítorí ìyà tí ọ̀ta à rẹ yóò fi jẹ ọ́ nígbà ìgbógun tì, ìwọ yóò jẹ, ẹran ara ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ.

54. Ènìyàn jẹ́jẹ́ àti onímọ̀ jùlọ kò ní ní àánú fún arákùnrin ara rẹ̀ tàbí ìyàwó tí ó fẹ́ràn tàbí àwọn ọmọ rẹ̀ tí o wà láàyè,

55. Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìpọ́njú tí àwọn ọ̀ta yóò fi pọ́n ọ lójú ní ìlú u rẹ.

Deutarónómì 28