4. Nítorí ó ti sọ níbìkan ní ti ọjọ́ kéje bayìí pé, “Ọlọ́run sì sinmi ní ọjọ́ keje kúrò nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.”
5. Àti níhìn yìí pẹ̀lú ó wí pé, “Wọn kì yóò wọ inú ìsinmi mi.”
6. Nítorí náà bí ó tí jẹ́ pé, ó ku kí àwọn kan wọ inú rẹ̀, àti àwọn tí a tí wàásù ìyìn rere náà fún ní ìṣáajú kò wọ inú rẹ̀ nítorí àìgbọ́ràn:
7. Àti pé, ó yan ọjọ́ kan, ó wí nínú ìwé Dáfídì pé, “Lònìí,” lẹ́yìn ìgbà pípẹ́ bẹ́ẹ̀; bí a tí wí niṣáájú,“Lònì-ín bí ẹ̀yín bá gbọ́ ohùn rẹ̀,ẹ má ṣe sé ọkàn yín le.”