Àìsáyà 56:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ohun tí Olúwa wí nìyìí:“Ẹ pa ìdájọ́ mọ́ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà,nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsíàti òdodo mi ni a ó fi hàn láìpẹ́ jọjọ.

2. Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí,ọkùnrin náà tí ó dì í mú ṣinṣin,tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bàá jẹ́,tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”

3. Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀mọ́ Olúwa sọ wí pé,“Olúwa yóò yà mí ṣọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.”Àti kí ìwẹ̀fà kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé“Igi gbígbẹ lásán ni mí.”

4. Nítorí pé ohun tí Olúwa wí nìyìí:“Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́,tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mití wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin

Àìsáyà 56