Àìsáyà 54:12-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Èmi yóò fi rúbísì ṣe odiì rẹ,àwọn ẹnu ọ̀nà ni a ó fi ohun èlò dáradára fún,àti àwọn ògiri rẹ pẹ̀lú òkúta iyebíye.

13. Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ ni Olúwa yóò kọ́,àlàáfíà àwọn ọmọ rẹ yóò jẹ́ ńlá àti púpọ̀.

14. Ní òdodo ni a ó fi ìdí rẹ kalẹ̀Ìwà ipá yóò jìnnà sí ọo kò ní bẹ̀rù ohunkóhunÌpayà la ó mú kúrò pátapáta;kò ní súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.

15. Bí ẹnikẹ́ni bá tilẹ̀ bá ọ jà, kò ní jẹ́ láti ọwọ́ọ̀ mi;ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ọ jà ni yóò túúbá fún ọ.

16. “Kíyèsí i, Èmi ni ó dá alágbẹ̀dẹtí ń fẹ́ iná èédú di èjò-inátí ó sì ń mú ohun èlò wá tí ó bá iṣẹ́ rẹ mu.Èmi náà sì ni ẹni tí ó dá apanirun láti ṣe iṣẹ́ ibi;

Àìsáyà 54