6. Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò mọ orúkọ mi;nítorí ní ọjọ́ náà, wọn yóò mọ̀pé Èmi ni ó ti sọ àṣọtẹ́lẹ̀ rẹ̀.Bẹ́ẹ̀ ni, Èmi ni.”
7. Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkèẹṣẹ̀ àwọn tí ó mú ìyìn rere ayọ̀ wá,tí wọ́n kéde àlàáfíà,tí ó mú ìyìn rere wá,tí ó kéde ìgbàlà,tí ó sọ fún Ṣíhónì pé,“Ọlọ́run rẹ ń jọba!”
8. Tẹ́tísílẹ̀! Àwọn olùṣọ́ rẹ gbé ohùn wọn ṣókèwọ́n kígbe papọ̀ fún ayọ̀.Nígbà tí Olúwa padà sí Ṣíhónì,wọn yóò rí i pẹ̀lú ojúu wọn.
9. Ẹ bú sí orin ayọ̀ papọ̀,ẹ̀yin ahoro Jérúsálẹ́mù,nítorí Olúwa ti tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú,ó sì ti ra Jérúsálẹ́mù padà.