Àìsáyà 51:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ,ẹni tí ó ta àwọn ọ̀runtí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé ṣọlẹ̀,tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́nítorí ìbínú àwọn aninilára,tí wọ́n sì gbọ́kàn lé ipanirun?Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?

14. Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọwọn kò ní kú sínú túbú wọn,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.

15. Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,tí ó ń ru òkun ṣókè tó bẹ́ẹ̀ tíìgbì rẹ̀ fi ń pariwo Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

16. Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹmo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí àyè rẹ̀,ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀,àti ẹni tí ó sọ fún Ṣhíónì pé,‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’ ”

17. Jí, jí!Gbéra nílẹ̀ Ìwọ Jérúsálẹ́mù,ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwakọ́ọ̀bù ìbínú rẹ̀,ìwọ tí o ti fà á mu dégẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀fèrè tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀ngbọ̀nọ́n.

18. Nínú gbogbo ọmọ tí ó bíkò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ sọ́nànínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.

Àìsáyà 51