Àìsáyà 37:20-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Nísinsìn yìí, Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ọ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”

21. Lẹ́yìn náà Àìṣáyà ọmọ Ámósì rán iṣẹ́ kan sí Heṣekáyà: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ pé: Nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Ṣenakérúbù ọba Áṣíríà,

22. èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀:“Wúndíá ọmọbìnrin Ṣíhónìkẹ́gàn ó sì fi ọ ṣe yẹ̀yẹ́.Ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mùmi oríi rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.

23. Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀ òdì sí?Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókètí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga?Sí Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì!

Àìsáyà 37