4. Kí ojú kí ó tì ọ́, ìwọ Ṣídónì àti ìwọàní ìwọ ilé-ààbò ti òkun,nítorí òkun ti sọ̀rọ̀:“Èmi kò tí ì wà ní ipò ìrọbí tàbí ìbímọ ríÈmi kò tí ì wọ àwọn ọmọkùnrintàbí kí n tọ́ àwọn ọmọbìnrin dàgbà rí.”
5. Nígbà tí ọ̀rọ̀ bá dé Éjíbítì,wọn yóò wà ní ìpayínkeke nípaìròyìn láti Tírè.
6. Kọjá wá sí Táṣíṣì;pohùnréré, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù.
7. Ǹjẹ́ èyí náà ni ìlú àríyáa yín,ògbólógbòò ìlú náà,èyí tí ẹṣẹ̀ rẹ̀ ti sìn ín lọláti lọ tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré.