2 Tẹsalóníkà 1:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Pọ́ọ̀lù, Sílà àti Tímótíù,Sí ìjọ Tẹsalóníkà, nínú Ọlọ́run Baba wa àti Jésù Kírísítì Olúwa:

2. Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run baba àti Jésù Kírísítì Olúwa.

3. Ó yẹ kí a máa dúpẹ́ nígbà gbogbo nítorí yín, ará, àní gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, nítorí pé ìgbàgbọ́ yín ń dàgbà gidigidi, àti ìfẹ́ olúkúlùkù yín gbogbo sí ara yín ń di púpọ̀.

2 Tẹsalóníkà 1