5. “Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri;tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
6. Ọ̀já isà-òkú yí mi káàkiri;ìkẹ́kùn ikú dojú kọ mí.
7. Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa,èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi.Ó sí gbóhùn mi láti tẹ́ḿpìlì rẹ̀igbe mí wọ etí rẹ̀.