2 Sámúẹ́lì 17:19-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Obìnrin rẹ̀ sì mú nǹkán ó fi bo kanga náà, ó sì sá àgbàdo sórí rẹ̀, a kò sì mọ̀.

20. Àwọn ìránṣẹ́ Ábúsálómù sì tọ obìnrin náà wá sí ilé náà, wọ́n sì béèrè pé, “Níbo ni Áhímásì àti Jónátanì gbé wà?”Obìnrin náà sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gòkè rékọjá ìṣàn odò náà.” Wọ́n sì wá wọn kiri, wọn kò sì rí wọn, wọ́n sì yípadà sí Jérúsálẹ́mù.

21. Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti lọ tán, àwọn ọkùnrin náà sì jáde kúrò nínú kànga, wọ́n sì lọ wọ́n sì rò fún Dáfídì ọba. Wọ́n sọ fún Dáfídì pé, “Dìde kí o sì gòkè odò kánkán: nítorí pé bayìí ni Áhítófélì gbìmọ̀ sí ọ.”

22. Dáfídì sì dìde, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì gòkè odò Jódánì: kí ilẹ̀ tó mọ́, ènìyàn kò kù tí kò gòkè odò Jódánì.

2 Sámúẹ́lì 17