25. Ọba sì wí fún Sádókù pé, “Sì tún gbé àpótí-ẹ̀rí Ọlọ́run náà padà sí ìlú: bí èmi bá rí ojú rere gbà lọ́dọ̀ Olúwa, yóò sì tún mú mi padà wá, yóò sì fi àpótí-ẹ̀rí náà hàn mí àti ibùgbé rẹ̀.
26. Ṣùgbọ́n bí òun bá sì wí pé, ‘Èmi kò ní inú dídùn sí ọ,’ wò ó, èmi nì yìí, jẹ́ kí òun ó ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí o ti tọ́ ní ojú rẹ̀.”
27. Ọba sì wí fún Sádókù àlùfáà pé, “Aríran ha kọ́ ni ọ́? Padà sí ìlú ní àlàáfíà, àti àwọn ọmọ rẹ méjèèjì pẹ̀lú rẹ, Áhímásì ọmọ rẹ, àti Jónátanì ọmọ Ábíátárì.
28. Wò ó, èmi ó dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà, títí ọ̀rọ̀ ó fi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá láti sọ fún mi.”
29. Sádókù àti Ábíátarì sì gbé àpótí-ẹ̀rí Ọlọ́run padà sí Jérúsálẹ́mù: wọ́n sì gbé ibẹ̀.