2 Ọba 7:18-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ó sì ti sẹlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyan Ọlọ́run ti ṣọ fún ọba: “Ní àsìkò yìí ní ọ̀la, òsùnwọ̀n ìyẹ̀fun ni a ó ta nì Ṣékélì kan àti òsùnwọ̀n méjì báálì ní Ṣékélì kan ní ẹnu ọ̀nà ibodè Ṣamáríà.”

19. Ìjòyè náà ti wí fún ènìyàn Ọlọ́run pé, “Wò ó, kó dà ti Olúwa bá sí fèrèsé ní ọ̀run, ṣé èyí lè ṣẹlẹ̀?” Ènìyàn Ọlọ́run sì ti dáhùn pé, “kìkì ojú rẹ ni ìwọ yóò fi rí i, Ṣùgbọ́n ìwọ kò ní jẹ ọ̀kan kan lára rẹ̀.”

20. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí fún un gẹ́lẹ́, nítorí tí àwọn ènìyàn tẹ̀ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ẹnu ibodè, ó sì kú.

2 Ọba 7