2 Ọba 24:18-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ṣedekáyà jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún mọ́kànlá. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Hámútalì ọmọbìnrin Jeremáyà; ó sì wá láti Líbínà.

19. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Jéhóíákínì ti ṣe.

20. Nítorí tí ìbínú Olúwa, ni gbogbo èyí ṣe sẹ sí Jérúsálẹ́mù, àti Júdà, ní òpin ó ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.Nísinsìn yìí Ṣedekíàyà sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Bábílónì.

2 Ọba 24