1. Nígbà tí ọba Ẹṣkáyà gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀ ó sì lọ sí àgọ́ Olúwa
2. Ó sì rán Eliákímù olùtọ́jú ààfin, Ṣébínà akọ̀wé àti olórí àlùfáà gbogbo wọn sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, sí ọ̀dọ̀ wòlíì Àìṣáyà ọmọ Ámósì.
3. Wọ́n sì sọ fún ún pé, “Èyí ni ohun tí Héṣékáyà sọ: ọjọ́ òní yí jẹ́ ọjọ́ ìpọ́njú àti ìbáwí àti ẹ̀gàn, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí ọmọdé wá sí ojú ìbímọ tí kò sì sí agbára láti fi bí wọn.