22. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yọ Heṣekáyà àti àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì kúrò lọ́wọ́ Senákéríbù ọba Ásíríà àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn mìíràn. Ó tọ́jú wọn ní gbogbo ọ̀nà.
23. Ọ̀pọ̀ mú ọrẹ wá sí Jérúsálẹ́mù fún Olúwa àti àwọn ẹ̀bùn iyebíye fún Heṣekáyà ọba Júdà. Láti ìgbà náà lọ gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè ni ó kàá sí.
24. Ní ọjọ́ wọ̀n nì Heṣekáyà ṣe àárẹ̀, ó sì dójú ikú. Ó gbàdúrà sí Olúwa, Tí ó dá a lóhùn, tí ó sì fún un ní àmì àgbàyanu.
25. Ṣùgbọ́n ọkàn Heṣekáyà ṣe ìgbéraga, kò sì kọbi ara síi inú rere tí a fi hàn án. Nítorí náà, ìbínú Olúwa wà lórí rẹ̀ àti lóri Júdà àti Jérúsálẹ́mù.
26. Nígbà náà Heṣekáyà ronú pìwàdà ní ti ìgbéraga ọkàn rẹ̀, àwọn ènìyàn Jérúsálẹ́mù sì ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí náà, ìbínú Olúwa kò wá sí orí wọn ní ìgbà àwọn ọjọ́ Heṣekáyà.