2 Kíróníkà 24:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Nísinsinyí, àwọn ọmọkùnrin, obìnrin búburú ni Ataláyà ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Báálì.

8. Nípasẹ̀ ọba, a ṣe àpótí wọ́n sì gbé e sí ìta, ní ẹnu ọ̀nà ilé Olúwa.

9. A ṣe ìkéde ní Júdà àti Jérúsálẹ́mù wí pé wọ́n gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa, owó orí tí Mósè ìránṣẹ́ Olúwa ti bèèrè lọ́wọ́ Ísírẹ́lì ní ihà.

10. Gbogbo àwọn ènìyàn mú gbogbo ìdá owó ti wọn wá pẹ̀lú ìdùnnú, wọ́n ń jù ú sínú àpótí títí tí ó fi kún.

11. Nígbà kígbà tí a bá gbé àpótí wọlé láti ọwọ́ àwọn ará Léfì sí ọwọ́ àwọn ìjòyè ọba, tí wọ́n bá sì rí wí pe owó ńlá wà níbẹ̀ àwọn akọ̀wé ọna àti ìjòyè olórí àlùfáà yóò wá láti kó owó rẹ̀ kúrò, wọn yóò sì dá a padà sí àyè rẹ̀. Wọ́n ṣe èyí déédéé, wọ́n sì kó iye owó ńlá.

2 Kíróníkà 24