1 Tímótíù 2:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Bí kò ṣe pẹ̀lú iṣẹ́ rere, èyí tí ó yẹ fún àwọn obìnrin tó jẹ́wọ́ pé wọ́n sin Ọlọ́run.

11. Jẹ́ kí obìnrin máa fi ìdákẹ́jẹ́ àti ìtẹríba gbogbo kọ́ ẹ̀kọ́.

12. Ṣùgbọ́n èmi kò fi àṣẹ fún obìnrin láti máa kọ́ni, tàbí láti pàṣẹ lórí ọkùnrin, bí kò ṣe kí ó dákẹ́jẹ́.

13. Nítorí Ádámù ni a kọ́ dá, lẹ́yìn náà, Éfà.

14. Ádámù kọ́ ni a tàn jẹ, ṣùgbọ́n obìnrin náà ni a tàn tí ó sì di ẹlẹ́ṣẹ̀.

1 Tímótíù 2