1 Sámúẹ́lì 26:2-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ṣọ́ọ̀lù sì dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Sífì ẹgbẹ̀ẹ́dógún àṣàyàn ènìyàn ni Ísírẹ́lì sì pẹ̀lú rẹ̀ láti wá Dáfídì ni ijù Sífì.

3. Ṣọ́ọ̀lù sì pàgọ́ rẹ̀ ní ibi òkè Hákílà tí o wà níwájú Jésímónì lójú ọ̀nà, Dáfídì sì jókòó ni ibi ijù náà, ó sì rí pé Ṣọ́ọ̀lù ń tẹ̀lé òun ni ijù náà.

4. Dáfídì sì rán àyọ́lẹ̀wò jáde, ó sì mọ nítòótọ́ pé Ṣọ́ọ̀lù ń bọ̀.

5. Dáfídì sì dìde, ó sì wá sí ibi ti Ṣọ́ọ̀lù pàgọ́ sí: Dáfídì rí ibi tí Ṣọ́ọ̀lù gbé dúbúlẹ̀ sí, àti Ábínérì ọmọ Nérì, olórí ogun rẹ̀: Ṣọ́ọ̀lù sì dùbúlẹ̀ láàrin àwọn kẹ̀kẹ́, àwọn ènìyàn náà sì pàgọ́ wọn yí i ká.

1 Sámúẹ́lì 26